Yoruba Paper 2 WASSCE (PC 2ND), 2018

Question 13

    Ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé lórí bí a ṣe ń lo ológò láti gba gbèsè láàrin àwọn Yorùbá ní ìgbà àtijọ́.


Observation

Candidates were required to explain ways of retrieving bad debts in traditional Yorùbá society.
Bí a ṣe ń lo Ológò/Adógò láti gba gbèsè láàrin àwọn Yorùbá ní ìgbà àtijọ́:

  1. Ológò/Adógo ni ẹni tí à ń lò láti gba gbèsè tí ẹni tí ó jẹ ni lówó kò bá fẹ́ẹ́ san owó náà.
  2. Olówó yóò rán ológò lọ sílé ajẹgbèsè láti lọ bá òun gba owó náà tipátipá.
  3. Àwọn tí a máa ń sáàbàá lò láti dógò ni àwọn alárùn bí ológòdò, adẹ́tẹ̀ àti eĺégbò ńlá.
  4. Ológò lè jẹ́ ẹlẹ́kẹ̀ẹ́ èébú tí ó lè bú ènìyàn dáradára, kí ó sì fi í ṣe ẹ̀sín/yẹ̀yẹ́.
  5. Bí ológò bá délé ajẹgbèsè, yóò dógò tì í títí tí yóò fi wá owó náà san.
  6. Oríṣiríṣi ọ̀nà ni ológò lè gbà dààmú ajẹgbèsè títí tí yóò fi rí owó náà san.
  7. Ológò lè má jẹ́ kí ajẹgbèsè jẹun; o lè ṣe ọ̀bùn sínú ilé ajẹgbèsè; ó lè sún sórí ibùsùn kan náà pẹ̀lú ajẹgbèsè.
  8. Bí ológò ti ń fòòró ẹ̀mí ajẹgbèsè ni yóò máa fòòró ẹ̀mí àwọn ará ilé rẹ̀ pẹ̀lú.
  9. Nígbà tí wàhálà bá sú àwọn ará ilé ajẹgbèsè, wọ́n lè dá owó náà jọ láti san gbèsè náà.
  10. Lára owó tí ológò bá gbà fún olówó ni olówo yóò ti yọ owó ọ̀yà rẹ̀ fún un.

Most candidates mistook Òṣómàáló for Ológo/Adógo. Ológo is a hired debt collector while Òṣómàáló is an Ìjẹ̀ṣà creditor who forcefully retrieves debt.