Yoruba Paper 2, Private Candidates 2019

Question 11

 

Ìṣẹ̀lẹ̀ wo ló fa ikú Jùwọ́n?.
Candidates were expected to narrate the episode that led to the death of Juwon.

Ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó fa ikú Jùwọ́n:
(i) Ọmọ tí Kúnbi bí fún Fẹ́mi ni wọ́n sọ ní Jùwọ́n.

(ii) Jùwọ́n ti ń rá kòrò káàkiri inú ilé wọn.

(iii) Ní ọjọ́ kan, Kúnbi wà nínú ilé ìdáná.

(iv) Fẹ́mi wà ní pálọ̀ tí ó ń wo eré bọ́ọ̀lù lórí ẹ̀rọ

móhùnmáwòrán/tẹlifíṣọ̀n.

(v) Jùwọ́n ń fi bọ́ọ̀lù ṣeré; ó ń rákòrò kiri.

(vi) Jùwọ́n rákòrò tẹ̀lé bọ́ọ̀lù wọ inú yàrá àwọn òbí rẹ̀.

(vii) Bọ́ọ̀lù yí wọ abẹ́ ibùsùn, Jùwọ́n rá kòrò tì í.

(viii) Nígbà tí ó dé abẹ́ ibùsùn, ó rí ìgò funfun kan tí nǹkan wà nínú rẹ̀.

(ix) Ó fà á síta, ó sì bẹ̀rẹ̀ síí fi ṣeré bí i bọ́ọ̀lù láì mọ̀ pé ìgò àdó ìyá rẹ̀ ni.

(x) Ó gbá a mọ́lẹ̀; ìgò fọ́; àdó sì jáde.

(xi) Ó fọwọ́ kan àdó, ó kígbe oró, ó nà gbalaja sílẹ̀.

(xii) Fẹ́mi sáré wọlé, ó gbé Jùwọ́n, ó di ilé-ìwòsàn ṣùgbọ́n ó ti dòkú.

Observation

 

Candidates who attempted the question did justice to it.